








Kacou Philippe ni a bí ní oṣù Kejìlá ọdún 1972 ní Katadji, ní ìjọba ìbílẹ̀ ti Sikensi ní Ivory Coast. Ọmọ agbe kan tí kò mọ̀ wé kọ ni. Lẹ́yìn ilé-ìwé alakọbẹrẹ, Kacou Philippe tẹ̀síwájú dé ọdún mẹ́rin péré ní ilé-ìwé girama. Láti ọdún 1992 sí 2002, ó lo púpọ̀ nínú àkókò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òṣìṣẹ́ ní àwọn ibi tí àwọn ènìyàn ti ń kọ́ ilé.
Ohun gbogbo bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ìran kan tí ó rí ní ọjọ́ 24 oṣù Kẹrin ọdún 1993. Ní ìbẹ̀rẹ̀, ó lọ sọ́dọ̀ àlùfáà Kátólíìkì kan láti béèrè ìtumọ̀ ìran náà. Lẹ́yìn náà, ó lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn Baptists tí ó gbé pẹ̀lú wọn fún oṣù mẹ́ta. Lẹ́yìn èyí, ó pàdé ẹgbẹ́ ìsọ̀kan ti William Branham, ajíhìnrere ará Amẹ́ríkà kan. Ó dúró pẹ̀lú ẹgbẹ́ náà gẹ́gẹ́ bí ọmọ ìjọ lasan láti ọdún 1993 sí 2002.
Kacou Philippe bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìwàásù níta gbangba ní oṣù Keje ọdún 2002, lẹ́yìn ìbẹ̀wò kejì ti áńgẹ́lì náà tí ó rí ní ọdún 1993. Ó sọ pé òun ni wòlíì ojiṣẹ́ ti igbe ọ̀gànjọ́, ní ìbámu pèlú Matthew 25 :6.
Gẹ́gẹ́ bí Wòlíì Kacou Philippe ṣe sọ, gbogbo àwọn ìjọ ń sin Èṣù ní orúkọ Jesu Kristi. Ó tún máa ń sọ ní ọ̀pọ̀ ìgbà nípa ìran mìíràn tí ó rí ní ọdún 1993, nínú èyí tí ó sọ pé ó rí àwọn aṣáájú ìjọ pẹ̀lú ìrísí àjèjì pé : “Ara wọn jẹ́ ara ènìyàn, ṣùgbọ́n orí wọn jẹ́ orí àwọn ẹranko oríṣìíríṣìí. Nígbà náà ni àwọn àríyànjiyàn àti àwọn ìjàkadì ìtakò àkọ́kọ́ bẹ̀rẹ̀.
Kacou Philippe ń wàásù nípa ọ̀pọ̀ àṣírí, bí àpẹẹrẹ pé : “Tí Ọlọ́run bá pa gbogbo ibi run pẹ̀lú Ìkún-omi ní àkókò Noah, báwo ni ibi ṣe tún padà wá sí ayé lẹ́yìn Ìkún-omi náà ?” Gbogbo ìwàásù yìí ni ìwé ìròyìn kan láti Cameroon tẹ jáde ní kíkún. Kacou Philippe sọ pé àwọn ọ̀rọ̀ rẹ̀ ní iye kan náà pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì inú Bíbélì.
Gẹ́gẹ́ bí Kacou Philippe ṣe kọ́ni, Ìjọ bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú Jòhánù Baptist, àti pé ìrìbọmi ìrònúpìwàdà ni. Lẹ́yìn náà ni ìrìbọmi ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀lú àwọn àpọ́sítélì ; lẹ́yìn náà ìrìbọmi ìdáláre nípa ìgbàgbọ́ pẹ̀lú Martin Luther ; lẹ́yìn náà ìrìbọmi àtunbi Ìjọ lẹ́yìn àwọn inúnibíni àkọ́kọ́ ti Róòmù ; lẹ́yìn náà ìrìbọmi fún isọdọmọ ; lẹ́yìn náà ìrìbọmi ìsọdimímọ́ pẹ̀lú John Wesley ; lẹ́yìn náà ìrìbọmi àtúnbí pẹ̀lú ẹ̀sìn Pẹ́ńtíkọ́sítì ; ìrìbọmi ìmúpadàbọ̀sípò pẹ̀lú William Branham, àti báyìí ìrìbọmi Ìpadàbọ̀sípò ohun gbogbo pẹ̀lú Wòlíì Kacou Philippe. Ó sì tẹnumọ̀ pé yàtọ̀ sí èyí, gbogbo ìrìbọmi mìíràn jẹ́ èké, kódà bí wọ́n bá ṣe é ní orúkọ Jesu Kristi tàbí ní orúkọ Baba, Ọmọ àti Ẹ̀mí Mímọ́ pẹ̀lú itẹbọmi ènìyàn.
Kacou Philippe ka Bíbélì sí dígí ẹ̀yìn ọkọ̀ ayọ́kẹ́lẹ́ tàbí ìwé ìtàn. Gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ, Bíbélì jẹ́ àkókù ìtàn ìṣáájú àwọn Júù àti Kristẹni, kò sì lè fún ènìyàn ní Ìyè Ayérayé rárá. Ó máa ń dáná sun gbogbo àwọn ẹ̀dà Bíbélì tí ó kà sí ewu fún ìgbàgbọ́, bíi Tob, King James, Thompson, Scofield àti Louis Segond. Kacou Philippe tún ṣe àlàyé tuntun nípa ohun tí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run jẹ́, nípa fífi ìyàtọ̀ hàn láàárín Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run (àwọn òtítọ́ tí a fihàn) àti ẹ̀kọ́ ẹ̀sìn (ìmọ̀ tí ènìyàn rí gbà nípasẹ̀ ọgbọ́n orí). Ó tún ṣe àlàyé tuntun nípa ìjẹ́ Ọlọ́run ti Jésù Kristi, ìjẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó gbọdọ̀ jẹ́ ní gbangba, ipò obìnrin nínú Ìjọ, ìrìbọmi omi, Ẹ̀mí Mímọ́, wòlíì, Bíbélì, ìbáṣepọ̀ láàárín Ìjọ àti Ìjọba àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ apá mìíràn ti ìgbàgbọ́ Kristẹni. Lórí èyí, ó kọ̀ láti dáhùn sí ìpè sí ẹ̀ka ọlọ́pàá tó ń ṣàkójọ ìwádìí àti ìròyìn nípa ààbò ti Ivory Coast pè é sí. Ó tún ṣe àlàyé tuntun fún gbogbo ẹ̀sìn Kristẹni nínú ìwé kan tí wọ́n ń pè ní Ìwé Wòlíì Kacou Philippe, tí a tẹ̀ jáde ní ìwọn mẹ́ta láti ọwọ́ ilé-iṣẹ́ ìtẹ̀wé Édilivre ní ilẹ̀ Faransé… Wo ìwé ìròyìn : Le Jour Plus N°3399 ti oṣu April 15, ọdún 2016 àti ìwé ìròyìn Le Sursaut N. ti oṣù April 15, ọdún 2016.
Ní oṣù Kẹta ọdún 2008, Kacou Philippe kó gbogbo àwọn olórí ẹ̀sìn ilẹ̀ rẹ̀ jọ, pẹ̀lú àwọn akọ̀ròyìn àti àwọn aṣojú awujọ fún ìpàdé kan nípa ẹ̀sìn Kristẹni, níbi tí ó ti ṣe ìdájọ́ ìjọ. Ìwé ìròyìn kan ṣàpèjúwe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí amòye ńlá nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run. Lẹ́yìn ìpàdé náà, ìwé ìròyìn kan kọ sí orí àkọlé rẹ̀ pé : “Wòlíì kan bọ́ aṣọ lára àwọn ènìyàn Ọlọ́run.” Gẹ́gẹ́ bí William Branham, Kacou Philippe sọ nípa ìwàláàyè agbára àìrídìmú kan tí ó sọ pé ó jẹ́ ti áńgẹ́lì ti 24 April ọdún 1993.
Ní ọdún 2008, àwọn ìwàásù Wòlíì Kacou Philippe bẹ̀rẹ̀ sí í túmọ̀ sí àwọn èdè míì. Àwọn ìwé ìròyìn sì bẹ̀rẹ̀ sí í tẹ àwọn ìwàásù rẹ̀ jáde ní pátápátá, títí dé àwọn orílẹ̀-èdè míì lẹ́yìn Ivory Coast. Ìwé ìròyìn kan ní ilẹ̀ Cameroon kọ sí orí àkọlé rẹ̀ pé : Kacou Philippe, Wòlíì kan tí ń tún ẹ̀sìn Kristẹni ṣe. Lórí àwọn ilé iṣẹ́ ìròyìn bíi Africa Number 1, àwọn àríyànjiyàn bẹ̀rẹ̀. Díẹ̀ lára àwọn ènìyàn dáhùn ní ọ̀nà àìtààrà, àwọn mìíràn sì ṣe é ní gbangba àti pẹ̀lú ìwà ipá. Àwọn mìíràn tún lọ jìnà síi, wọ́n ń mú àwọn ẹ̀kọ́ Kacou Philippe wá lẹ́kọ̀ọ̀kan kí wọ́n lè tako wọn dáadáa. Ní ọjọ́ 13 oṣù Karùn-ún ọdún 2016, ni àwọn aláṣẹ orílẹ̀-èdè Ivory Coast mú Kacou Philippe ní ilé rẹ̀ nítorí ìtakò sí àṣẹ ìjọba, ìmúnilórí sí ìkórìíra ẹ̀sìn àti ìfarahàn ìgbóná ẹ̀sìn. Ó lo ọjọ́ márùún àti òru márùún ní ìjókòó lórí àga ijoko ní ọ́fíìsì ẹ̀ka ọlọ́pàá ìròyìn àpapọ̀ ti Ivory Coast. Lẹ́yìn náà, ó tún lo ọjọ́ méjì àti òru méjì ní abẹ́ ilẹ̀ ilé-iṣẹ́ ọlọ́pàá ńlá ti Abidjan, àti oṣù mẹ́ta ní ẹ̀wọ̀n tó tóbi jùlọ ní Abidjan, kí ó tó gba òmìnira rẹ̀ padà ní òru ọjọ́ 16 oṣù Kẹjọ ọdún 2016, ṣùgbọ́n wọ́n gba gbogbo ẹ̀tọ́ ìlú rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ rẹ̀, wọ́n sì dín in lọ́wọ́ láti wàásù Ìhìnrere fún ọdún márùn-ún. Àwọn ilé iṣẹ́ ìròyìn ilẹ̀ Togo àti Cameroon pe ìdájọ́ náà ní ohun tí kò ṣe kedere. Lẹ́yìn náà, díẹ̀ lára àwọn olórí ẹ̀sìn ní Ivory Coast jẹ́wọ́ pé àwọn ló wà lẹ́yìn mímú àti ìtìmọ́lé rẹ̀.
Fún Kacou Philippe, iṣẹ́ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ ní ìpele pàtàkì méjì tàbí ìdánimọ̀ méjì. Ìpele àkọ́kọ́, èyí tí ó ka sí ogún láti ọwọ́ baba rẹ̀, William Marrion Branham, ni ìmúṣẹ Matthew 25 :6, ó sì kó gbogbo àwọn ìfihàn inú orí 1 títí dé orí 154 ti ìwé rẹ̀ tí a ń pè ní « Ìwé ti Wòlíì Kacou Philippe ». Ìpele kejì, èyí tí ó jẹ́ iṣẹ́ àsọtẹ́lẹ̀, àlá àti ìran, fún ipadabọ sípò àwọn ìfihàn láti orí 155 títí dé orí 162 ti ìwé náà. Lẹ́yìn náà, láti orí 163, pẹ̀lú iye àwọn orí tí kò tíì dájú fún ìsinsìnyí, ni gbogbo àwọn ẹ̀rí ìwòsàn àti iṣẹ́ ìyanu tí ń jẹ́rìí sí iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀ nípasẹ̀ oríṣìíríṣìí iṣẹ́ ìwòsàn ní ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè káàkiri ayé, títí di ìmúṣẹ ìran pápá ńlá tí ó rí ní ọdún 1993.
Gẹ́gẹ́ bí Kacou Philippe ṣe sọ, àlá àti ìran ni èdè àṣírí láàárín àwọn ọlọ́run àti ènìyàn, pẹ̀lú Ọlọ́run Olódùmarè. Ó fi àlá àti ìran wé òfin ọkọ̀ ojú pópó àti àwọn àmì ojú ọ̀nà nínú ìrìn-àjò aráyé sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ; nítorí náà, àìka àlá tàbí ìran sí jẹ́ láti kẹ́gàn Ọlọ́run. Nítorí náà, gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ, èyí jẹ́ kókó-ọrọ̀ tí a gbọ́dọ̀ máa kọ́ ní gbogbo àwọn ṣọ́ọ̀ṣì àti ẹ̀sìn káàkiri ayé, kí a lè fi hàn fún àwọn onígbàgbọ́ bí àlá àti ìran ṣe ṣe pàtàkì. Síbẹ̀síbẹ̀, ìtumọ̀ àlá àti ìran gbọ́dọ̀ jẹ́ pẹ̀lú ọgbọ́n púpọ̀ àti ìṣọ́ra gidigidi láti ọwọ́ olórí ẹ̀sìn kankan, nítorí pé ẹ̀bùn láti ọdọ Ọlọ́run ni a fi ń ṣe irú iṣẹ́ bẹ́ẹ̀.
Ní ọjọ́ kàrùn-ún oṣù kẹfà ọdún 2022, Kacou Philippe rí ìran kan nínú èyí tí áńgẹ́lì kan fún un ní ìwé kékeré aláwọ̀ búlúù tí ó sì pa á láṣẹ láti lọ sí South Africa. Ní àkókò tí Ọlọ́run yàn, ó lóye pé ìwé aláwọ̀ búlúù náà túmọ̀ sí passport, àti pé lẹ́yìn ọdún méjìdínlógún ju bẹ́ẹ̀ lọ nínú iṣẹ́ òjíṣẹ́ láì fi Ivory Coast sílẹ̀, Ọlọ́run ń pa á láṣẹ báyìí láti bẹ̀rẹ̀ àwọn ìrìn-àjò míṣọ́nnárì, àti pé ó yẹ kí ó kọ́kọ́ lọ sí South Africa láti gba ẹ̀bùn ìwòsàn tí William Marrion Branham fi sílẹ̀. Nípasẹ̀ ọ̀pọ̀ àlá àti ìran, ó tún lóye pé ó yẹ kí ó ṣètò àwọn iṣẹ́ ìwòsàn àti iṣẹ́ ìyanu láì gba owó. Áńgẹ́lì kan tún pa á láṣẹ ní ọdún 2021 pé kó má ṣe gba owó tàbí irú ẹ̀bùn kankan lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, fún ìdí kankan, nígbà iṣẹ́ ìwòsàn rẹ̀. Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìwòsàn rẹ̀ àkọ́kọ́ ní South Africa ní oṣù kẹta ọdún 2025 ní ọ̀pọ̀ ìlú, pẹ̀lú Johannesburg, Pretoria, Middelburg àti Zebediela. Lẹ́yìn náà, ní oṣù kẹrin ọdún 2025, ó lọ sí Zimbabwe lẹ́yìn díẹ̀ lára àwọn ìṣòro kékeré tó ní pẹ̀lú gbigba visa. Àwọn iṣẹ́ ìwòsàn ní Zimbabwe wáyé ní àwọn ìlú Harare àti Bulawayo láti ọjọ́ kẹrìnlá (14) sí ọjọ́ kọkànlélógún (21) oṣù kẹrin ọdún 2025. Gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ ẹ̀rí ṣe sọ, ọ̀pọ̀ àwọn aláìsàn — afọ́jú, arọ, aláìlera ẹsẹ̀, àwọn tí wọ́n ní HIV àti adití — gba ìwòsàn lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ tàbí ní ọjọ́ díẹ̀ lẹ́yìn náà. Ọ̀pọ̀ àwọn ilé iṣẹ́ ìròyìn ilẹ̀ South Africa, Zimbabwe, Ivory Coast, Benin, Cameroun àti Central Africa, pẹ̀lú àwọn ìwé ìròyìn ńlá bíi The Herald àti The Chronicle, sọ nípa àwọn ìrìn-àjò Wòlíì Kacou Philippe sí South Africa àti Zimbabwe. Gẹ́gẹ́ bí Kacou Philippe ṣe sọ, ìrìn-àjò iṣẹ́ ìhìnrere rẹ̀ sí South Africa lẹ́yìn náà sí Zimbabwe, pẹ̀lú àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ̀, jọra pátápátá sí ti William Branham ní àkókò rẹ̀ ní ọdún 1951. Ìfarajọ̀ àwọn iṣẹ́ ìyanu wọ̀nyí lè jẹ́rìí sí nípa kíka tàbí fífetí sí orí 163 àti 164 inú ìwé Wòlíì Kacou Philippe àti ìwé ẹ̀rí ìjọba náà, William Branham, a Prophet Visits South Africa tí Julius Stadsklev kọ. Ìfarajọ̀ yìí yóò mú ènìyàn dé ìpinnu pé angẹli Odò Ohio náà ni angẹli kan náà tí ó wà pẹ̀lú Wòlíì Kacou Philippe. Lẹ́yìn Zimbabwe, a ti ṣètò pé Kacou Philippe yóò lọ sí Gabon ní oṣù June ọdún 2025, ṣùgbọ́n ìjọba Gabon kọ̀ láti fún un ní visa nítorí àwọn aṣáájú ẹ̀sìn tí wọ́n tako àwọn iṣẹ́ ìwòsàn ọ̀fẹ́ ti Wòlíì Kacou Philippe fún oríṣìíríṣìí ìdí, ṣùgbọ́n pàápàá jùlọ nítorí pé gbogbo iṣẹ́ ìwòsàn rẹ̀ jẹ́ ọ̀fẹ́ pátápátá, nínú ìgbọràn pípé sí ìtọ́nisọ́nà angẹli kan nínú ìran ní ọdún 2021. Èyí ló fa ìfagilé ètò rẹ̀ ní Gabon àti àwọn ètò ní àwọn orílẹ̀-èdè míì bíi Benin, Togo, Cameroun, Congo Brazzaville àti Congo Kinshasa.
Orísun: https://plus.wikimonde.com/wiki/Kacou_Philippe”
(Tí a wàásù ní ọjọ́ Sunday, August 18, 2002 ní Locodjro, Abidjan – Ivory Coast)
(Tí a wàásù ní ọjọ́ Sunday, October 20, 2002 ní Locodjro, Abidjan – Ivory Coast)
(Tí a wàásù ní ọjọ́ àìkú, ọjọ́ kẹwàá [10] oṣù kọkànlá, ọdún 2002 ní Locodjro, Abidjan, Ivory Coast)
(Ti a wàásù ní òwúrọ̀ ọjọ aiku ojo keedogun osu kewaa Sunday, ọdún 2002 ní Locodjro, Abidjan – Ivory Coast)
(Tí a wàásù ní òwúrọ̀ ọjọ́ àìkú, ọjọ́ kejìlélógún [22] oṣù kẹwàá, ọdún 2002 ní Locodjro, Abidjan – Ivory Coast)
(Tí wàásù ní òwúrọ̀ ọjọ́ àìkú, ọjọ́ Kejì, oṣù kọkànlá , ọdún 2003 ní Locodjro, Abidjan – Ivory Coast)
(Tí a wàásù ní ọjọ́ àìkú ọjọ Kejìlá [12], oṣù kínní, ọdún 2003 ní Locodjro, Abidjan Ivory Coast)
(Tí a wàásù ní òwúrọ̀ Sunday, May 4, 2003 ní Locodjro, Abidjan, Ivory Coast)
(Tí a wàásù ní òwúrọ̀ ọjọ́ àìkú, ọjọ́ kẹtàlélógún [23], oṣù Kejì, ọdún 2003 ní Locodjro, Abidjan – Ivory Coast)
(Tí a wàásù ní òwúrọ̀ ojọ́ Sunday, December 1, 2002 ní Locodjro, Abidjan – Ivory Coast)
(Tí á wàásù ní òwúrọ̀ ọjọ́ Sunday, April 27, 2003, lẹ́yìn náà ní Locodjro, Abidjan, Ivory Coast lọ́dún 2006)